33. Àwọn igi igbó yóo kọrin ayọ̀níwájú OLUWA, nítorí ó wá láti ṣe ìdájọ́ ayé.
34. Ẹ fi ọpẹ́ fún OLUWA nítorí pé ó ṣeun,ìfẹ́ rẹ̀ tí kìí yẹ̀ sì wà títí lae!
35. Ẹ kígbe pé, “Gbà wá, Ọlọrun, olùgbàlà wa,kó wa jọ, sì gbà wá láàrin àwọn orílẹ̀-èdè,kí á lè máa dúpẹ́, kí á máa yin orúkọ mímọ́ rẹ,kí á sì máa ṣògo ninu ìyìn rẹ.
36. Ẹni ìyìn ni OLUWA, Ọlọrun Israẹli,lae ati laelae!”Gbogbo àwọn eniyan sì dáhùn pe, “Amin”, wọ́n sì yin OLUWA.