Kronika Kinni 16:26-32 BIBELI MIMỌ (BM)

26. Nítorí pé ère lásán ni àwọn orílẹ̀-èdè yòókù sọ di ọlọrun,ṣugbọn OLUWA ló dá ọ̀run.

27. Ògo ati agbára yí i ká,ayọ̀ ati ìyìn sì kún Tẹmpili rẹ̀.

28. Ẹ fi ògo fún OLUWA, gbogbo ayé,ẹ gbé ògo ati agbára wọ̀ ọ́!

29. Ẹ fi ògo tí ó yẹ orúkọ OLUWA fún un,ẹ mú ọrẹ wá sí iwájú rẹ̀!Ẹ sin OLUWA pẹlu ẹwà mímọ́,

30. ẹ wárìrì níwájú rẹ̀, gbogbo ayé,ó fi ìdí ayé múlẹ̀ gbọningbọnin kò sì lè yẹ̀ lae.

31. Kí inú ọ̀run kí ó dùn,kí ayé kí ó yọ̀,kí wọ́n sọ láàrin àwọn orílẹ̀-èdè pé “OLUWA jọba!”

32. Kí òkun ati ohun gbogbo tó wà ninu rẹ̀ hó yèè,kí pápá oko búsáyọ̀, ati gbogbo ẹ̀dá tó wà ninu rẹ̀.

Kronika Kinni 16