Kronika Kinni 16:25-29 BIBELI MIMỌ (BM)

25. OLUWA tóbi, ìyìn tọ́ sí i lọpọlọpọó sì yẹ kí á bọ̀wọ̀ fún un ju gbogbo àwọn oriṣa lọ.

26. Nítorí pé ère lásán ni àwọn orílẹ̀-èdè yòókù sọ di ọlọrun,ṣugbọn OLUWA ló dá ọ̀run.

27. Ògo ati agbára yí i ká,ayọ̀ ati ìyìn sì kún Tẹmpili rẹ̀.

28. Ẹ fi ògo fún OLUWA, gbogbo ayé,ẹ gbé ògo ati agbára wọ̀ ọ́!

29. Ẹ fi ògo tí ó yẹ orúkọ OLUWA fún un,ẹ mú ọrẹ wá sí iwájú rẹ̀!Ẹ sin OLUWA pẹlu ẹwà mímọ́,

Kronika Kinni 16