Kronika Kinni 1:27-34 BIBELI MIMỌ (BM)

27. Abramu, tí a tún ń pè ní Abrahamu.

28. Àwọn ọmọ Abrahamu ni Isaaki ati Iṣimaeli.

29. Àkọsílẹ̀ ìran wọn nìyí: Nebaiotu ni àkọ́bí Iṣimaeli, lẹ́yìn náà ni ó bí Kedari, Adibeeli, ati Mibisamu;

30. Miṣima, Duma ati Masa; Hadadi ati Tema;

31. Jeturi, Nafiṣi, ati Kedema.

32. Abrahamu ní obinrin kan tí ń jẹ́ Ketura. Ó bí àwọn ọmọ mẹfa wọnyi fún Abrahamu: Simirani, Jokiṣani ati Medani; Midiani, Iṣibaki ati Ṣua. Àwọn ọmọ ti Jokiṣani ni: Ṣeba ati Dedani.

33. Àwọn ọmọ marun-un tí Midiani bí ni Efa, Eferi ati Hanoku, Abida ati Elidaa. Gbogbo wọn jẹ́ arọmọdọmọ Ketura.

34. Abrahamu ni baba Isaaki. Àwọn ọmọ Isaaki meji ni Esau ati Jakọbu.

Kronika Kinni 1