Joẹli 2:13-16 BIBELI MIMỌ (BM)

13. Ìrònúpìwàdà tòótọ́ ni mò ń fẹ́,kì í ṣe pé kí ẹ fa aṣọ yín ya nìkan.”Ẹ yipada sí OLUWA Ọlọrun yín,nítorí olóore-ọ̀fẹ́ ati aláàánú ni.Kì í yára bínú,Ó kún fún ìfẹ́ tí kì í yẹ̀,a sì máa dárí ẹ̀ṣẹ̀ ji eniyan.

14. Ó ṣeéṣe kí Ọlọrun ṣàánú, kí ó yí ibinu rẹ̀ pada,kí ó sì tú ibukun rẹ̀ sílẹ̀,kí ẹ lè rú ẹbọ ohun jíjẹ ati ẹbọ ohun mímu fún OLUWA Ọlọrun yín.

15. Ẹ fọn fèrè ní òkè Sioni,ẹ kéde ààwẹ̀ kí ẹ sì pe àpéjọ.

16. Ẹ pe gbogbo eniyan jọ,kí ẹ sì ya ìjọ eniyan sí mímọ́.Ẹ pe àwọn àgbààgbà jọ,ẹ kó àwọn ọmọde ati àwọn ọmọ ọwọ́ jọ.Kí ọkọ iyawo jáde láti inú yàrá rẹ̀,kí iyawo àṣẹ̀ṣẹ̀gbé náà jáde ninu yàrá rẹ̀.

Joẹli 2