Jobu 5:5-12 BIBELI MIMỌ (BM)

5. Àwọn tí ebi ń pa níí jẹ ìkórè oko rẹ̀,bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ààrin ẹ̀gúnni ó ti mú un jáde,àwọn olójúkòkòrò a sì máa wá ohun ìní rẹ̀ kiri.

6. Ìṣòro kì í hù láti inú erùpẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni ìyọnu kì í ti inú ilẹ̀ jáde.

7. A bí eniyan sinu wahalabí ẹ̀ta iná tí ń ta sókè.

8. “Ní tèmi, n óo máa wá OLUWA,n óo fọ̀rọ̀ mi lé Ọlọrun lọ́wọ́;

9. ẹni tíí ṣe ohun ńlátí eniyan kò lè rídìí,ati àwọn ohun ìyanu tí kò lóǹkà.

10. A máa rọ òjò sórí ilẹ̀,a sì máa bomi rin oko.

11. A máa gbé àwọn onírẹ̀lẹ̀ ga,a sì máa pa àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ mọ́.

12. A máa da ète àwọn alárèékérekè rú,kí wọn má baà lè yọrí ètekéte wọn.

Jobu 5