Jobu 4:8-14 BIBELI MIMỌ (BM)

8. Bí èmi ti rí i sí ni pé,ẹni tí ó kọ ẹ̀ṣẹ̀ mọ́ ebè,tí ó sì gbin wahala,yóo kórè ìyọnu.

9. Èémí Ọlọrun níí pa wọ́n run,ninu ibinu rẹ̀, wọ́n a sì ṣègbé.

10. Ọlọrun fi òpin sí igbe kinniun,ati bíbú tí kinniun ń bú ramúramù,ó sì wọ́ àwọn ẹgbọ̀rọ̀ kinniun léyín.

11. Kinniun alágbára a máa kú,nítorí àìrí ẹran pa jẹ,àwọn ọmọ abo kinniun a sì fọ́nká.

12. “Nisinsinyii wọ́n fọ̀rọ̀ kan tó mi létímo gbọ́ wúyẹ́-wúyẹ́ rẹ̀.

13. Ninu ìran lóru,nígbà tí àwọn eniyan sùn fọnfọn,

14. ìbẹ̀rùbojo mú mi,gbogbo ara mi sì ń gbọ̀n rìrì.

Jobu 4