Jobu 39:15-19 BIBELI MIMỌ (BM)

15. ó gbàgbé pé ẹnìkan le tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ kí wọn sì fọ́,ati pé ẹranko ìgbẹ́ lè fọ́ wọn.

16. Ògòǹgò kò náání àwọn ọmọ rẹ̀,ó ń ṣe sí wọn bí ẹni pé kì í ṣe òun ló bí wọn,kò bìkítà bí wahala rẹ̀ tilẹ̀ já sí asán;

17. nítorí pé Ọlọrun kò fún un ní ọgbọ́n ati òye.

18. Ṣugbọn nígbà tí ó bá ṣetán ati sáré,a máa fi ẹṣin ati ẹni tí ó gùn ún ṣe yẹ̀yẹ́.

19. “Ṣé ìwọ ni o fún ẹṣin lágbára,tí o sì fi agbára ṣe gọ̀gọ̀ sí i lọ́rùn?

Jobu 39