Jobu 38:1-6 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Nígbà náà ni OLUWA dá Jobu lóhùn láti inú ìjì líle.

2. Ó bi í pé,“Ta ni ẹni tí ń bu ẹnu àtẹ́ lu ìmọ̀ràn,tí ń sọ̀rọ̀ tí kò ní ìmọ̀?

3. Nisinsinyii, múra gírí bí ọkunrin,mo ní ìbéèrè kan láti bí ọ, o óo sì dá mi lóhùn.

4. Níbo lo wà, nígbà tí mo fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀?Bí o bá mọ ìgbà náà, sọ fún mi.

5. Ta ló ṣe ìdíwọ̀n rẹ̀–ṣebí o mọ̀ ọ́n, dá mi lóhùn!Àbí ta ló ta okùn ìwọ̀n sórí rẹ̀?

6. Orí kí ni a gbé ìpìlẹ̀ rẹ̀ lé,àbí ta ló fi òkúta igun rẹ̀ sọlẹ̀;

Jobu 38