Jobu 36:21-27 BIBELI MIMỌ (BM)

21. Ṣọ́ra kí o má yipada sí ìwà ẹ̀ṣẹ̀,tí ó wù ọ́ ju ìjìyà lọ.

22. “Wò ó, a gbé OLUWA ga ninu agbára rẹ̀;ta ni olùkọ́ tí ó dàbí rẹ̀?

23. Ta ló ń sọ ohun tí yóo ṣe fún un,tabi kí ó sọ fún un pé, ‘Ohun tí o ṣe yìí kò dára?’

24. Ranti láti gbé iṣẹ́ rẹ̀ ga,tí àwọn eniyan ń kọrin nípa rẹ̀.

25. Gbogbo eniyan ti rí i;àwọn tí wọ́n wà ní òkèèrè ń wò ó.

26. Wò ó, Ọlọrun tóbi lọ́ba, ju ìmọ̀ wa lọ,kò sí ẹni tí ó lè mọ ọjọ́ orí rẹ̀.

27. “Ó fa ìkán omi sókè láti inú ilẹ̀,ó sọ ìkùukùu di òjò,

Jobu 36