17. “Ṣugbọn, ìdájọ́ eniyan burúkú dé bá ọ,ọwọ́ ìdájọ́ ati òdodo sì ti tẹ̀ ọ́.
18. Ṣọ́ra kí ibinu má baà sọ ọ́ di ẹlẹ́yà,kí títóbi àbẹ̀tẹ́lẹ̀ sì mú ọ ṣìnà.
19. Igbe ati agbára rẹ kò lè gbà ọ́ kúrò ninu ìpọ́njú.
20. Má máa dúró, kí o máa retí ọjọ́ alẹ́,nígbà tí à ń pa àwọn eniyan run.
21. Ṣọ́ra kí o má yipada sí ìwà ẹ̀ṣẹ̀,tí ó wù ọ́ ju ìjìyà lọ.
22. “Wò ó, a gbé OLUWA ga ninu agbára rẹ̀;ta ni olùkọ́ tí ó dàbí rẹ̀?
23. Ta ló ń sọ ohun tí yóo ṣe fún un,tabi kí ó sọ fún un pé, ‘Ohun tí o ṣe yìí kò dára?’
24. Ranti láti gbé iṣẹ́ rẹ̀ ga,tí àwọn eniyan ń kọrin nípa rẹ̀.