Jobu 36:17-24 BIBELI MIMỌ (BM)

17. “Ṣugbọn, ìdájọ́ eniyan burúkú dé bá ọ,ọwọ́ ìdájọ́ ati òdodo sì ti tẹ̀ ọ́.

18. Ṣọ́ra kí ibinu má baà sọ ọ́ di ẹlẹ́yà,kí títóbi àbẹ̀tẹ́lẹ̀ sì mú ọ ṣìnà.

19. Igbe ati agbára rẹ kò lè gbà ọ́ kúrò ninu ìpọ́njú.

20. Má máa dúró, kí o máa retí ọjọ́ alẹ́,nígbà tí à ń pa àwọn eniyan run.

21. Ṣọ́ra kí o má yipada sí ìwà ẹ̀ṣẹ̀,tí ó wù ọ́ ju ìjìyà lọ.

22. “Wò ó, a gbé OLUWA ga ninu agbára rẹ̀;ta ni olùkọ́ tí ó dàbí rẹ̀?

23. Ta ló ń sọ ohun tí yóo ṣe fún un,tabi kí ó sọ fún un pé, ‘Ohun tí o ṣe yìí kò dára?’

24. Ranti láti gbé iṣẹ́ rẹ̀ ga,tí àwọn eniyan ń kọrin nípa rẹ̀.

Jobu 36