Jobu 33:9-14 BIBELI MIMỌ (BM)

9. O ní o mọ́, o kò ní ẹ̀ṣẹ̀,ara rẹ mọ́ o kò sì ṣe àìdára kankan.

10. Sibẹ Ọlọrun wá ẹ̀sùn sí ọ lẹ́sẹ̀,ó sọ ọ́ di ọ̀tá rẹ̀,

11. ó kan ààbà mọ́ ọ lẹ́sẹ̀,ó sì ń ṣọ́ ìrìn rẹ.

12. “Jobu, n óo dá ọ lóhùn,nítorí pé bí o ti wí yìí, bẹ́ẹ̀ kọ́ lọ̀rọ̀ rí.Ọlọrun ju eniyan lọ.

13. Kí ló dé tí ò ń fi ẹ̀sùn kàn ánpé kò ní fèsì kankan sí ọ̀rọ̀ rẹ?

14. Nítorí Ọlọrun sọ̀rọ̀ bákan, ó tún tún un sọ bámìíràn,ṣugbọn kò sí ẹni tí ó yé.

Jobu 33