Jobu 33:14-22 BIBELI MIMỌ (BM)

14. Nítorí Ọlọrun sọ̀rọ̀ bákan, ó tún tún un sọ bámìíràn,ṣugbọn kò sí ẹni tí ó yé.

15. Ninu àlá, lójú ìran ní ààrin òru,nígbà tí eniyan bá sun oorun àsùnwọra, lórí ibùsùn wọn,

16. Ọlọrun a máa ṣí wọn létí,a máa kìlọ̀ fún wọn, a sì máa dẹ́rùbà wọ́n,

17. kí ó lè dá wọn lẹ́kun ìṣe wọn,kí ó lè gba ìgbéraga lọ́wọ́ wọn;

18. kí ó lè yọ ọkàn eniyan kúrò ninu ọ̀fìn ìparun,kí ó má baà kú ikú idà.

19. “OLUWA a máa fi ìrora jẹ eniyan níyà lórí ibùsùn rẹ̀;a sì máa kó ìnira bá egungun rẹ̀.

20. Tóbẹ́ẹ̀ tí ẹnu rẹ̀ yóo kọ oúnjẹ,oúnjẹ àdídùn óo sì rùn sí i.

21. Eniyan á rù hangangan,wọn a sì fẹ́rẹ̀ lè máa ka egungun rẹ̀.

22. Ọkàn rẹ̀ á súnmọ́ ibojì,ẹ̀mí rẹ̀ a sì súnmọ́ àwọn iranṣẹ ikú.

Jobu 33