13. Kí ló dé tí ò ń fi ẹ̀sùn kàn ánpé kò ní fèsì kankan sí ọ̀rọ̀ rẹ?
14. Nítorí Ọlọrun sọ̀rọ̀ bákan, ó tún tún un sọ bámìíràn,ṣugbọn kò sí ẹni tí ó yé.
15. Ninu àlá, lójú ìran ní ààrin òru,nígbà tí eniyan bá sun oorun àsùnwọra, lórí ibùsùn wọn,
16. Ọlọrun a máa ṣí wọn létí,a máa kìlọ̀ fún wọn, a sì máa dẹ́rùbà wọ́n,
17. kí ó lè dá wọn lẹ́kun ìṣe wọn,kí ó lè gba ìgbéraga lọ́wọ́ wọn;
18. kí ó lè yọ ọkàn eniyan kúrò ninu ọ̀fìn ìparun,kí ó má baà kú ikú idà.