13. Ẹ ṣọ́ra, kí ẹ má baà wí pé, ‘A ti di ọlọ́gbọ́n,Ọlọrun ló lè ṣe ìdájọ́ rẹ̀, kì í ṣe eniyan.’
14. Èmi kọ́ ni Jobu ń bá wí, ẹ̀yin ni,n kò sì ní dá a lóhùn bí ẹ ṣe dá a lóhùn.
15. “Ọkàn wọn dàrú, wọn kò sì lè fèsì mọ́,bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní ohun kan láti sọ.
16. Ṣé kí n dúró,nítorí pé wọ́n dúró láìfèsì?
17. Èmi náà óo fèsì lé e,n óo sì sọ èrò ọkàn tèmi.
18. Mo ní ọ̀rọ̀ pupọ láti sọ,Ṣugbọn ẹ̀mí tí ó wà ninu mi ló ń kó mi ní ìjánu.
19. Ọ̀rọ̀ kún inú mi bí ọtí inú ìgò,ó fẹ́ ru síta bí ọtí inú ìgò aláwọ.