Jobu 28:9-12 BIBELI MIMỌ (BM)

9. “Eniyan á dá ọwọ́ rẹ̀ lé òkúta akọ, á gbẹ́ ẹ,á sì hú òkè ńlá tìdítìdí.

10. Á gbẹ́ ihò sinu àpáta,ojú rẹ̀ a sì tó àwọn ìṣúra iyebíye.

11. Á dí orísun àwọn odò,tóbẹ́ẹ̀ tí wọn kò fi lè sun,á sì wá àwọn ohun tí ó pamọ́ jáde.

12. Ṣugbọn níbo ni a ti lè rí ọgbọ́n?Níbo sì ni ìmọ̀ wà?

Jobu 28