Jobu 27:15-19 BIBELI MIMỌ (BM)

15. Àwọn ọmọ tí wọn bá gbẹ̀yìn rẹ̀,àjàkálẹ̀ àrùn ni yóo pa wọ́n,àwọn opó wọn kò sì ní ṣọ̀fọ̀ wọn.

16. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ń kó fadaka jọ bí erùpẹ̀,tí ó sì to aṣọ jọ bí amọ̀;

17. olódodo ni yóo wọ aṣọ tí ó bá kó jọ,àwọn aláìṣẹ̀ ni yóo pín fadaka rẹ̀.

18. Ilé tí ó kọ́ dàbí òwú aláǹtakùn,àní bí àgọ́ àwọn tí wọn ń ṣọ́nà.

19. A ti máa wọlé sùn pẹlu ọrọ̀ tẹ́lẹ̀, ṣugbọn kò ní rí bẹ́ẹ̀ fún un mọ́.Nígbà tí ó bá la ojú rẹ̀, gbogbo ọrọ̀ rẹ̀ yóo ti fò lọ.

Jobu 27