Jobu 26:4-10 BIBELI MIMỌ (BM)

4. Ta ló ń kọ yín ni ohun tí ẹ̀ ń sọ wọnyi?Irú ẹ̀mí wo sì ní ń gba ẹnu yín sọ̀rọ̀?

5. “Àwọn òkú wárìrì nísàlẹ̀.Omi ati àwọn olùgbé inú rẹ̀ pẹlu ń gbọ̀n rìrì.

6. Kedere ni isà òkú rí níwájú Ọlọrun,bẹ́ẹ̀ ni ìparun kò farasin.

7. Ó na ìhà àríwá sórí òfuurufú,ó sì so ayé rọ̀ sí òfuurufú.

8. Ó di omi papọ̀ ninu ìkùukùu rẹ̀ tí ó nípọn,sibẹ ìkùukùu kò fà ya.

9. Ó dí ojú òṣùpá,ó sì fi ìkùukùu bò ó.

10. Ó ṣe òbìrìkítí kan sórí omi,ó fi ṣe ààlà láàrin òkùnkùn ati ìmọ́lẹ̀.

Jobu 26