Jobu 24:20-25 BIBELI MIMỌ (BM)

20. Wọn á gbàgbé wọn láàrin ìlú,ẹnikẹ́ni kì í ranti orúkọ wọn mọ́,bẹ́ẹ̀ ni ẹni ibi ṣe é wó lulẹ̀ bí ìtì igi.’

21. Wọ́n ń jẹ oúnjẹ àgàn tí kò bímọ,wọn kò sì ṣe rere fún opó.

22. Sibẹsibẹ Ọlọrun fi ẹ̀mí gígùn fún alágbára nípa agbára rẹ̀;wọn á gbéra nígbà tí ayé bá sú wọn.

23. Ọlọrun ń dáàbò bò wọ́n, ó ń ràn wọ́n lọ́wọ́,ó sì ń pa wọ́n mọ́ ni ọ̀nà wọn.

24. A gbé wọn ga fún ìgbà díẹ̀,lẹ́yìn náà, a rẹ̀ wọ́n sílẹ̀,wọn á rọ, wọn á sì rẹ̀ dànù bí ewé,a ké wọn kúrò bí orí ọkà bàbà.

25. Bí kò bá rí bẹ́ẹ̀, kí ẹnìkan já mi nírọ́,kí ó sì fi hàn pé ìsọkúsọ ni mò ń sọ.”

Jobu 24