Jobu 22:9-16 BIBELI MIMỌ (BM)

9. O lé àwọn opó jáde lọ́wọ́ òfo,o sì ṣẹ́ aláìní baba lápá.

10. Nítorí náà ni okùn dídẹ fi yí ọ ká,tí jìnnìjìnnì sì bò ọ́ lójijì.

11. Ìmọ́lẹ̀ rẹ ti di òkùnkùn, o kò ríran,ìgbì omi sì bò ọ́ mọ́lẹ̀.

12. “Ṣebí Ọlọrun wà lókè ọ̀runÓ ń wo àwọn ìràwọ̀ nísàlẹ̀àní àwọn tí wọ́n ga jùlọ,bí ó ti wù kí wọ́n ga tó!

13. Sibẹsibẹ ò ń bèèrè pé, ‘Kí ni Ọlọrun mọ̀?’Ṣé ó lè ṣe ìdájọ́ láti inú òkùnkùn biribiri?

14. Ìkùukùu tí ó nípọn yí i ká,tóbẹ́ẹ̀ tí kò lè ríran,ó sì ń rìn ní òfuurufú ojú ọ̀run.

15. “Ṣé ọ̀nà àtijọ́ ni ìwọ óo máa tẹ̀lé;ọ̀nà tí àwọn ẹni ibi rìn?

16. A gbá wọn dànù, kí àkókò wọn tó tó,a ti gbá ìpìlẹ̀ wọn lọ.

Jobu 22