Jobu 22:5-19 BIBELI MIMỌ (BM)

5. Ṣebí ìwà ibi rẹ ló pọ̀;tí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kò sì lópin?

6. O gba nǹkan ìdógò lọ́wọ́ àwọn arakunrin rẹ láìnídìí,O bọ́ wọn sí ìhòòhò goloto.

7. O kò fún aláàárẹ̀ ní omi mu,o kọ̀ láti fún ẹni tí ebi ń pa ní oúnjẹ.

8. Ẹni tí ó lágbára gba ilẹ̀,ẹni tí ó lọ́lá sì ń gbé inú rẹ̀.

9. O lé àwọn opó jáde lọ́wọ́ òfo,o sì ṣẹ́ aláìní baba lápá.

10. Nítorí náà ni okùn dídẹ fi yí ọ ká,tí jìnnìjìnnì sì bò ọ́ lójijì.

11. Ìmọ́lẹ̀ rẹ ti di òkùnkùn, o kò ríran,ìgbì omi sì bò ọ́ mọ́lẹ̀.

12. “Ṣebí Ọlọrun wà lókè ọ̀runÓ ń wo àwọn ìràwọ̀ nísàlẹ̀àní àwọn tí wọ́n ga jùlọ,bí ó ti wù kí wọ́n ga tó!

13. Sibẹsibẹ ò ń bèèrè pé, ‘Kí ni Ọlọrun mọ̀?’Ṣé ó lè ṣe ìdájọ́ láti inú òkùnkùn biribiri?

14. Ìkùukùu tí ó nípọn yí i ká,tóbẹ́ẹ̀ tí kò lè ríran,ó sì ń rìn ní òfuurufú ojú ọ̀run.

15. “Ṣé ọ̀nà àtijọ́ ni ìwọ óo máa tẹ̀lé;ọ̀nà tí àwọn ẹni ibi rìn?

16. A gbá wọn dànù, kí àkókò wọn tó tó,a ti gbá ìpìlẹ̀ wọn lọ.

17. Wọ́n sọ fún Ọlọrun pé,‘Fi wá sílẹ̀, kí ni ìwọ Olodumare lè fi wá ṣe?’

18. Sibẹsibẹ ó fi ìṣúra dáradára kún ilé wọn–ṣugbọn ìmọ̀ràn ẹni ibi jìnnà sí mi.

19. Àwọn olódodo rí i, inú wọn dùn,àwọn aláìlẹ́bi fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà,

Jobu 22