Jobu 20:8-15 BIBELI MIMỌ (BM)

8. Yóo parẹ́ bí àlá,yóo sì di àwátì,yóo pòórá bí ìran tí a rí lóru.

9. Ojú tí ó ti ń rí i tẹ́lẹ̀ kò ní rí i mọ́,ààyè rẹ̀ yóo sì ṣófo.

10. Àwọn ọmọ rẹ̀ yóo máa wá ojurere àwọn aláìní,wọn yóo sì san ohun tí baba wọn gbà lọ́wọ́ aláìní pada.

11. Bí ó tilẹ̀ dàbí ọ̀dọ́, tí ó lágbára,sibẹ yóo lọ sí ibojì, yóo sì di erùpẹ̀.

12. Bí ọ̀rọ̀ ìkà tilẹ̀ dùn ní ẹnu rẹ̀,tí ó sì fi pamọ́ sí abẹ́ ahọ́n rẹ̀,

13. bí ó tilẹ̀ lọ́ra láti sọ ọ́ jáde,tí ó pa ẹnu mọ́,

14. sibẹsibẹ oúnjẹ rẹ̀ a máa dà á ninu rú,ó sì ti dàbí oró ejò paramọ́lẹ̀ ninu rẹ̀.

15. Gbogbo owó tí ó kó jẹ ni ó tún ń pọ̀ jáde;Ọlọrun ní ń pọ̀ wọ́n jáde ninu ikùn rẹ̀.

Jobu 20