Jobu 20:14-22 BIBELI MIMỌ (BM)

14. sibẹsibẹ oúnjẹ rẹ̀ a máa dà á ninu rú,ó sì ti dàbí oró ejò paramọ́lẹ̀ ninu rẹ̀.

15. Gbogbo owó tí ó kó jẹ ni ó tún ń pọ̀ jáde;Ọlọrun ní ń pọ̀ wọ́n jáde ninu ikùn rẹ̀.

16. Yóo mu oró ejò,ahọ́n paramọ́lẹ̀ yóo pa á.

17. Kò ní gbádùn oyin ati wàrà tí ń ṣàn bí odò.

18. Kò ní jẹ èrè wahala rẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni kò ní gbádùn èrè tí ó bá jẹ nídìí òwò rẹ̀.

19. Nítorí pé ó ti tẹ aláìní mọ́lẹ̀,ó sì ti pa wọ́n tì sí apákanó sì fi ipá gba ilé tí kò kọ́.

20. Nítorí pé oníwọ̀ra ni,tí ọkàn rẹ̀ bá nàró sí nǹkankan,kò lè pa á mọ́ra.

21. Kì í jẹ àjẹṣẹ́kù,nítorí náà, ọlá rẹ̀ kò le tọ́jọ́.

22. Ninu ọlá ńlá rẹ̀ yóo wà ninu àhámọ́,ìbànújẹ́ yóo máa fi tagbára-tagbára bá a jà.

Jobu 20