Jobu 20:11-16 BIBELI MIMỌ (BM)

11. Bí ó tilẹ̀ dàbí ọ̀dọ́, tí ó lágbára,sibẹ yóo lọ sí ibojì, yóo sì di erùpẹ̀.

12. Bí ọ̀rọ̀ ìkà tilẹ̀ dùn ní ẹnu rẹ̀,tí ó sì fi pamọ́ sí abẹ́ ahọ́n rẹ̀,

13. bí ó tilẹ̀ lọ́ra láti sọ ọ́ jáde,tí ó pa ẹnu mọ́,

14. sibẹsibẹ oúnjẹ rẹ̀ a máa dà á ninu rú,ó sì ti dàbí oró ejò paramọ́lẹ̀ ninu rẹ̀.

15. Gbogbo owó tí ó kó jẹ ni ó tún ń pọ̀ jáde;Ọlọrun ní ń pọ̀ wọ́n jáde ninu ikùn rẹ̀.

16. Yóo mu oró ejò,ahọ́n paramọ́lẹ̀ yóo pa á.

Jobu 20