Jobu 17:8-12 BIBELI MIMỌ (BM)

8. Èyí ya àwọn olódodo lẹ́nu,aláìlẹ́bi sì dojú kọ ẹni tí kò mọ Ọlọrun.

9. Sibẹsibẹ olódodo kò fi ọ̀nà rẹ̀ sílẹ̀,ẹni tí ọwọ́ rẹ̀ mọ́ sì ń lágbára sí i.

10. Ṣugbọn ní tiyín, bí ẹ tilẹ̀ ṣe jù bẹ́ẹ̀ lọ,n kò ní ka ẹnikẹ́ni kún ọlọ́gbọ́n láàrin yín.

11. “Ọjọ́ ayé mi ti dópin, èrò ọkàn mi ti dàrú,àwọn ohun tí ọkàn mi ń fẹ́ sì ti di asán.

12. Wọ́n sọ òru di ọ̀sán,wọ́n ń sọ pé, ‘Ìmọ́lẹ̀ kò jìnnà sí òkùnkùn.’

Jobu 17