Jobu 15:24-29 BIBELI MIMỌ (BM)

24. Ìdààmú ati ìrora dẹ́rùbà á,wọ́n ṣẹgun rẹ̀, bí ọba tí ó múra ogun.

25. Nítorí pé ó ṣíwọ́ sókè sí Ọlọrun,o sì ṣe oríkunkun sí Olodumare,

26. ó ń ṣe oríkunkun sí i,ó sì gbé apata tí ó nípọn lọ́wọ́ láti bá a jà;

27. nítorí pé ó sanra tóbẹ́ẹ̀ tí ojú rẹ̀ yíbò,ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ sì jẹ́ kìkì ọ̀rá.

28. Ó ń gbé ìlú tí ó ti di ahoro,ninu àwọn ilé tí eniyan kò gbọdọ̀ gbé,àwọn ilé tí yóo pada di òkítì àlàpà.

29. Kò ní ní ọrọ̀,ohun tí ó bá ní, kò ní pẹ́ lọ́wọ́ rẹ̀,òun alára kò sì ní fìdí múlẹ̀.

Jobu 15