Jobu 14:17-22 BIBELI MIMỌ (BM)

17. O óo di àwọn ẹ̀ṣẹ̀ mi sinu àpò,o óo sì bo àwọn àìdára mi mọ́lẹ̀.

18. “Ṣugbọn òkè ńlá ṣubú, ó sì rún wómúwómú,a sì ṣí àpáta nídìí kúrò ní ipò rẹ̀.

19. Bí omi ṣe é yìnrìn òkúta,tí àgbàrá sì í wọ́ erùpẹ̀ ilẹ̀ lọ,bẹ́ẹ̀ ni o óo ṣe sọ ìrètí eniyan di òfo.

20. O ṣẹgun rẹ̀ títí lae, ó sì kọjá lọ,o yí àwọ̀ rẹ̀ pada, o sì mú kí ó lọ.

21. Wọ́n dá àwọn ọmọ rẹ̀ lọ́lá, ṣugbọn kò mọ̀,a rẹ̀ wọ́n sílẹ̀, sibẹ kò rí i.

22. Ìrora ara rẹ̀ nìkan ló mọ̀,ọ̀fọ̀ ara rẹ̀ nìkan ni ó ń ṣe.”

Jobu 14