22. Sọ wí pé,“Òkú eniyan yóo sùn lọ nílẹ̀ bí ìgbọ̀nsẹ̀ lórí pápá tí ó tẹ́jú,ati bíi ìtí ọkà lẹ́yìn àwọn tí wọn ń kórè ọkà,kò sì ní sí ẹni tí yóo kó wọn jọ. OLUWA ló sọ bẹ́ẹ̀.”
23. OLUWA ní, “Kí ọlọ́gbọ́n má fọ́nnu nítorí ọgbọ́n rẹ̀,kí alágbára má fọ́nnu nítorí agbára rẹ̀;kí ọlọ́rọ̀ má sì fọ́nnu nítorí ọrọ̀ rẹ̀.
24. Ṣugbọn ẹni tí ó bá fẹ́ fọ́nnu,ohun tí ó lè máa fi fọ́nnu ni pé òun ní òyeati pé òun mọ̀ pé, èmi OLUWA ni OLUWA tí ń ṣe ẹ̀tọ́,tí sì ń fi ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ ati òdodo hàn lórí ilẹ̀ ayé;nítorí pé àwọn nǹkan bẹ́ẹ̀ ni mo ní inú dídùn sí.”