Jeremaya 51:8-11 BIBELI MIMỌ (BM)

8. Babiloni ṣubú lójijì, ó sì fọ́;ẹ sun ẹkún arò nítorí rẹ̀!Ẹ fi ìwọ̀ra pa á lára nítorí ìrora rẹ̀,bóyá ara rẹ̀ yóo yá.

9. À bá wo Babiloni sàn,ṣugbọn a kò rí i wòsàn.Ẹ pa á tì, ẹ jẹ́ kí á lọ,kí olukuluku máa lọ sí ilẹ̀ rẹ̀;nítorí ẹjọ́ tí a dá a ti dé òkè ọ̀run,a sì ti gbé e sókè dé ojú ọ̀run.”

10. OLUWA ti dá wa láre;ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á lọ ròyìn iṣẹ́ OLUWA Ọlọrun wa ní Sioni.

11. Ẹ pọ́n ọfà yín!Ẹ gbé asà yín!Nítorí OLUWA ti ru ẹ̀mí àwọn ọba Media sókè,nítorí pé ó ti pinnu láti pa Babiloni run.Ẹ̀san OLUWA ni, ẹ̀san nítorí tẹmpili rẹ̀ tí wọ́n wó.

Jeremaya 51