Jeremaya 51:3-6 BIBELI MIMỌ (BM)

3. Kí tafàtafà má kẹ́ ọrun rẹ̀,kí ó má sì gbé ẹ̀wù irin rẹ̀ wọ̀.Má ṣe dá àwọn ọdọmọkunrin rẹ̀ sí,pa gbogbo àwọn ọmọ ogun rẹ̀ run patapata.

4. Kí wọ́n ṣubú, kí wọ́n sì kú ní ilẹ̀ Kalidea,kí wọ́n gún wọn ní àgúnyọ láàrin ìgboro.

5. Nítorí pé OLUWA àwọn ọmọ ogun, Ọlọrun Israẹli ati Juda kò kọ̀ wọ́n sílẹ̀;ṣugbọn ilẹ̀ Kalidea kún fún ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀,tí wọ́n dá sí Ẹni Mímọ́ Israẹli.

6. Ẹ sá kúrò láàrin Babiloni,kí olukuluku sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ̀!Ẹ má parun nítorí ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ Babiloni;nítorí àkókò ẹ̀san OLUWA nìyí,yóo sì san ẹ̀san fún Babiloni.

Jeremaya 51