Jeremaya 49:5-8 BIBELI MIMỌ (BM)

5. Wò ó! N óo kó ìpayà bá ọ,láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tí wọ́n yí ọ ká;èmi OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun ni mo sọ bẹ́ẹ̀.Gbogbo yín ni yóo fọ́nká,tí olukuluku yóo sì yà sí ọ̀nà tirẹ̀,kò sì ní sí ẹni tí yóo kó àwọn tí ń sá fún ogun jọ.

6. “Ṣugbọn lẹ́yìn náà, n óo dá ire àwọn ará Amoni pada.Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

7. Ohun tí OLUWA àwọn ọmọ ogun sọ nípa Edomu nìyí: Ó ní,“Ṣé kò sí ọgbọ́n ní Temani mọ́ ni?Àbí àwọn amòye kò ní ìmọ̀ràn lẹ́nu mọ́?Ṣé ọgbọ́n ti rá mọ́ wọn ninu ni?

8. Ẹ̀yin ará Dedani, ẹ pada kíá, ẹ máa sálọ.Ẹ wọ inú ihò lọ, kí ẹ lọ máa gbébẹ̀!Nítorí pé ní ìgbà tí mo bá jẹ ìran Esau níyà, n óo mú kí ibi dé bá wọn.

Jeremaya 49