Jeremaya 49:28-31 BIBELI MIMỌ (BM)

28. OLUWA sọ nípa Kedari ati àwọn ìjọba Hasori tí Nebukadinesari ọba Babiloni ṣẹgun pé,“Ẹ dìde kí ẹ gbógun ti Kedari!Ẹ pa àwọn ará ìlà oòrùn run!

29. Ogun yóo kó àgọ́ wọn ati àwọn ẹran ọ̀sìn wọn lọ,ati àwọn aṣọ àgọ́, ati ohun ìní wọn;Ọ̀tá yóo kó ràkúnmí wọn lọ,àwọn eniyan yóo máa kígbe sí wọn pé,‘Ìpayà wà ní gbogbo àyíká.’

30. “Ẹ̀yin ará Hasori, ẹ sá,ẹ lọ jìnnà réré, kí ẹ sì máa gbé inú ọ̀gbun.Nítorí pé Nebukadinesari, ọba Babiloni ń pète ibi si yín,ó ti pinnu ibi si yín.

31. Ó ní, ‘Ẹ dìde kí ẹ gbógun ti orílẹ̀-èdè tí ó wà ní alaafia, ati láìléwu,ìlú tí ó dá dúró tí kò sì ní ìlẹ̀kùn tabi ọ̀pá ìdábùú ìlẹ̀kùn fún ààbò.’

Jeremaya 49