Jeremaya 14:21-22 BIBELI MIMỌ (BM)

21. Má ta wá nù nítorí orúkọ rẹ,má sì fi àbùkù kan ìtẹ́ rẹ tí ó lógo.Ranti majẹmu tí o bá wa dá,ranti, má sì ṣe dà á.

22. Ninu gbogbo àwọn ọlọrun èké tí àwọn orílẹ̀-èdè ń sìn,ǹjẹ́ ọ̀kan wà tí ó lè mú kí òjò rọ̀?Àbí ojú ọ̀run ní ń fúnrarẹ̀ rọ ọ̀wààrà òjò?OLUWA Ọlọrun wa, ṣebí ìwọ ni?Ìwọ ni a gbẹ́kẹ̀lé,nítorí ìwọ ni o ṣe gbogbo nǹkan wọnyi.

Jeremaya 14