Jeremaya 14:18-22 BIBELI MIMỌ (BM)

18. Bí mo bá jáde lọ sí ìgbèríko,àwọn tí wọ́n fi idà pa ni wọ́n kún bẹ̀!Bí mo bá sì wọ ààrin ìlú,àwọn tí ìyàn di àìsàn sí lára ni wọ́n kún bẹ̀.Nítorí àwọn wolii ati àwọn alufaa ń lọ káàkiri gbogbo ilẹ̀ náà,wọn kò sì mọ ohun tí wọn ń ṣe.’ ”

19. OLUWA, ṣé o ti kọ Juda sílẹ̀ patapata ni?Àbí Sioni ti di ohun ìríra lọ́kàn rẹ?Kí ló dé tí o fi lù wá,tóbẹ́ẹ̀ tí ọ̀rọ̀ tiwa kọjá ìwòsàn?À ń retí alaafia, ṣugbọn ire kankan kò dé.À ń retí àkókò ìwòsàn, ṣugbọn ìpayà ni a rí.

20. OLUWA, a mọ ìwà burúkú wa,ati ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wa,nítorí a ti ṣẹ̀ ọ́.

21. Má ta wá nù nítorí orúkọ rẹ,má sì fi àbùkù kan ìtẹ́ rẹ tí ó lógo.Ranti majẹmu tí o bá wa dá,ranti, má sì ṣe dà á.

22. Ninu gbogbo àwọn ọlọrun èké tí àwọn orílẹ̀-èdè ń sìn,ǹjẹ́ ọ̀kan wà tí ó lè mú kí òjò rọ̀?Àbí ojú ọ̀run ní ń fúnrarẹ̀ rọ ọ̀wààrà òjò?OLUWA Ọlọrun wa, ṣebí ìwọ ni?Ìwọ ni a gbẹ́kẹ̀lé,nítorí ìwọ ni o ṣe gbogbo nǹkan wọnyi.

Jeremaya 14