Jeremaya 10:23-25 BIBELI MIMỌ (BM)

23. OLUWA, mo mọ̀ pé ọ̀nà ẹ̀dá kò sí ní ọwọ́ ara rẹ̀.Kò sí ní ìkáwọ́ ẹni tí ń rìn láti tọ́ ìṣísẹ̀ ara rẹ̀.

24. Tọ́ mi sọ́nà, OLUWA,ṣugbọn lọ́nà ẹ̀tọ́ ni kí o bá mi wí,kì í ṣe pẹlu ibinu rẹ,kí o má baà sọ mí di ẹni ilẹ̀.

25. Àwọn orílẹ̀-èdè tí wọn kò mọ̀ ọ́,ni kí o bínú sí kí ó pọ̀,ati àwọn tí wọn kì í jọ́sìn ní orúkọ rẹ;nítorí pé wọ́n ti jẹ Jakọbu run,wọ́n jẹ ẹ́ ní àjẹrun patapata,wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ̀ di ahoro.

Jeremaya 10