Ìwé Òwe 9:3-8 BIBELI MIMỌ (BM)

3. Ó ti rán àwọn iranṣẹbinrin rẹ̀kí wọn lọ máa kígbe lórí àwọn òkè láàrin ìlú pé:

4. “Ẹ yà síbí ẹ̀yin òpè!”Ó sọ fún ẹni tí kò lọ́gbọ́n pé,

5. “Máa bọ̀, wá jẹ lára oúnjẹ mi,kí o sì mu ninu ọtí waini tí mo ti pò.

6. Fi àìmọ̀kan sílẹ̀, kí o sì yè,kí o máa rin ọ̀nà làákàyè.”

7. Ẹni tí ń tọ́ oníyẹ̀yẹ́ eniyan sọ́nà fẹ́ kan àbùkù,ẹni tí ń bá ìkà eniyan wí ń wá ìfarapa fún ara rẹ̀.

8. Má ṣe bá oníyẹ̀yẹ́ eniyan wí,kí ó má baà kórìíra rẹ,bá ọlọ́gbọ́n wí, yóo sì fẹ́ràn rẹ.

Ìwé Òwe 9