Ìwé Òwe 8:25-32 BIBELI MIMỌ (BM)

25. Kí á tó dá àwọn òkè ńlá sí ààyè wọn,kí àwọn òkè kéékèèké tó wà, ni mo ti wà.

26. Kí Ọlọrun tó dá ayé, ati pápá oko,kí ó tó dá erùpẹ̀ ilẹ̀.

27. Mo wà níbẹ̀ nígbà tí ó dá ojú ọ̀run sí ààyè rẹ̀,tí ó ṣe àmì bìrìkìtì sórí ibú,ní ibi tí ó dàbí ẹni pé ilẹ̀ ati ọ̀run ti pàdé,

28. nígbà tí ó ṣe awọsanma lọ́jọ̀,tí ó fi ìpìlẹ̀ orísun omi sọ ilẹ̀,

29. nígbà tí ó pààlà sí ibi tí òkun gbọdọ̀ kọjá,kí omi má baà kọjá ààyè rẹ̀.Nígbà tí ó sàmì sí ibi tí ìpìlẹ̀ ayé wà,

30. èmi ni oníṣẹ́ ọnà tí mo wà lọ́dọ̀ rẹ̀,Inú mi a máa dùn lojoojumọ,èmi a sì máa yọ̀ níwájú rẹ̀ nígbà gbogbo.

31. Mo láyọ̀ ninu ayé tí àwọn ẹ̀dá alààyè ń gbé,inú mi sì ń dùn sí àwọn ọmọ eniyan.

32. “Nisinsinyii, ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ fetí sí mi,ayọ̀ ń bẹ fún àwọn tí ń rìn ní ọ̀nà mi.

Ìwé Òwe 8