21. Èmi a máa fún àwọn tí wọ́n fẹ́ mi ní ọrọ̀,n óo máa mú kí ìṣúra wọn kún.
22. Ní ìbẹ̀rẹ̀ ìṣẹ̀dá ayé ni OLUWA ti dá mi,kí ó tó bẹ̀rẹ̀ àwọn iṣẹ́ àrà rẹ̀.
23. Láti ayébáyé ni a ti yàn mí,láti ìbẹ̀rẹ̀, kí á tó dá ayé rárá.
24. Kí ibú omi tó wà ni mo ti wà,nígbà tí kò tíì sí àwọn orísun omi.
25. Kí á tó dá àwọn òkè ńlá sí ààyè wọn,kí àwọn òkè kéékèèké tó wà, ni mo ti wà.
26. Kí Ọlọrun tó dá ayé, ati pápá oko,kí ó tó dá erùpẹ̀ ilẹ̀.
27. Mo wà níbẹ̀ nígbà tí ó dá ojú ọ̀run sí ààyè rẹ̀,tí ó ṣe àmì bìrìkìtì sórí ibú,ní ibi tí ó dàbí ẹni pé ilẹ̀ ati ọ̀run ti pàdé,
28. nígbà tí ó ṣe awọsanma lọ́jọ̀,tí ó fi ìpìlẹ̀ orísun omi sọ ilẹ̀,
29. nígbà tí ó pààlà sí ibi tí òkun gbọdọ̀ kọjá,kí omi má baà kọjá ààyè rẹ̀.Nígbà tí ó sàmì sí ibi tí ìpìlẹ̀ ayé wà,
30. èmi ni oníṣẹ́ ọnà tí mo wà lọ́dọ̀ rẹ̀,Inú mi a máa dùn lojoojumọ,èmi a sì máa yọ̀ níwájú rẹ̀ nígbà gbogbo.
31. Mo láyọ̀ ninu ayé tí àwọn ẹ̀dá alààyè ń gbé,inú mi sì ń dùn sí àwọn ọmọ eniyan.