Ìwé Òwe 8:19-25 BIBELI MIMỌ (BM)

19. Èso mi dára ju wúrà dáradára lọ,àyọrísí mi sì dára ju ojúlówó fadaka lọ.

20. Ọ̀nà òdodo ni èmi ń rìn,ojú ọ̀nà tí ó tọ́ ni mò ń tọ̀.

21. Èmi a máa fún àwọn tí wọ́n fẹ́ mi ní ọrọ̀,n óo máa mú kí ìṣúra wọn kún.

22. Ní ìbẹ̀rẹ̀ ìṣẹ̀dá ayé ni OLUWA ti dá mi,kí ó tó bẹ̀rẹ̀ àwọn iṣẹ́ àrà rẹ̀.

23. Láti ayébáyé ni a ti yàn mí,láti ìbẹ̀rẹ̀, kí á tó dá ayé rárá.

24. Kí ibú omi tó wà ni mo ti wà,nígbà tí kò tíì sí àwọn orísun omi.

25. Kí á tó dá àwọn òkè ńlá sí ààyè wọn,kí àwọn òkè kéékèèké tó wà, ni mo ti wà.

Ìwé Òwe 8