Ìwé Òwe 7:13-24 BIBELI MIMỌ (BM)

13. Yóo bá dì mọ́ ọmọkunrin tí kò gbọ́n náà, yóo fi ẹnu kò ó lẹ́nu,yóo wí pẹlu ainitiju pé,

14. “Mo ti rú ẹbọ alaafia,mo sì ti san ẹ̀jẹ́ mi lónìí.

15. Nítorí náà, mo wá pàdé rẹ,mo fi ìlara wá ọ, mo sì rí ọ.

16. Mo ti tẹ́ aṣọ fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ aláràbarà ti ilẹ̀ Ijipti sórí ibùsùn mi.

17. Mo tú turari olóòórùn dídùn ati òjíá, aloe ati sinamoni, sórí ibùsùn mi.

18. Wá, jẹ́ kí á ṣeré ìfẹ́títí ilẹ̀ yóo fi mọ́,jẹ́ kí á fi ìfẹ́ gbádùn ara wa.

19. Ọkọ mi kò sí nílé,ó ti lọ sí ìrìn àjò, ọ̀nà rẹ̀ sì jìn.

20. Ó mú owó pupọ lọ́wọ́,kò ní dé títí òṣùpá yóo fi di àrànmọ́jú.”

21. Ó rọ̀ ọ́ pẹlu ọpọlọpọ ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn,ó fi ọ̀rọ̀ dídùn mú un.

22. Lẹsẹkẹsẹ, ọmọkunrin náà bẹ̀rẹ̀ sí tẹ̀lé e,bíi mààlúù tí wọn ń fà lọ pa,tabi bí àgbọ̀nrín tí ó tẹsẹ̀ bọ tàkúté,

23. títí tí ọfà fi wọ̀ ọ́ ninubí ẹyẹ tí ń yára bọ́ sinu okùn,láì mọ̀ pé ó lè ṣe ikú pa òun.

24. Nisinsinyii, ẹ fetí sílẹ̀, ẹ̀yin ọmọ mi,ẹ farabalẹ̀ gbọ́ nǹkan tí mò ń sọ.

Ìwé Òwe 7