Ìwé Òwe 5:4-9 BIBELI MIMỌ (BM)

4. ṣugbọn níkẹyìn ọ̀rọ̀ rẹ̀ á korò bí iwọ,ẹnu rẹ̀ á sì mú bí idà olójú meji.

5. Ẹsẹ̀ rẹ̀ ń dà gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ lọ sinu ikú,ìgbésẹ̀ rẹ̀ sì lọ tààrà sinu ibojì.

6. Ó kọ̀ láti rin ọ̀nà ìyè,ọ̀nà rẹ̀ wọ́, kò sì mọ̀.

7. Nisinsinyii, ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi,ẹ má sì kọ ọ̀rọ̀ sí mi lẹ́nu.

8. Ẹ jìnnà sí alágbèrè obinrin,kí ẹ má tilẹ̀ súnmọ́ ẹnu ọ̀nà rẹ̀,

9. kí ẹ má baà gbé ògo yín fún ẹlòmíràn,kí ẹ sì fi ìgbé ayé yín lé aláìláàánú lọ́wọ́.

Ìwé Òwe 5