Ìwé Òwe 4:23-27 BIBELI MIMỌ (BM)

23. Ṣọ́ra pẹlu èrò ọkàn rẹ,nítorí èrò ọkàn ni orísun ìyè.

24. Má lọ́wọ́ ninu ọ̀rọ̀ ìsọkúsọ,sì jìnnà sí ọ̀rọ̀ àgàbàgebè.

25. Jẹ́ kí ojú rẹ máa wo ọ̀kánkán,kí o sì kọjú sí ibi tí ò ń lọ tààrà.

26. Kíyèsí ìrìn ẹsẹ̀ rẹ,gbogbo ọ̀nà rẹ yóo sì là.

27. Má ṣe yà sí ọ̀tún tabi sí òsì,yipada kúrò ninu ibi.

Ìwé Òwe 4