Ìwé Òwe 30:22-27 BIBELI MIMỌ (BM)

22. ẹrú tí ó jọba,òmùgọ̀ tí ó jẹun yó,

23. obinrin tí ayé kórìíra tí ó wá rí ọkọ fẹ́,ati iranṣẹbinrin tí ó gba ọkọ mọ́ ọ̀gá rẹ̀ lọ́wọ́.

24. Àwọn nǹkan mẹrin kan wà tí wọ́n kéré ninu ayé,sibẹsibẹ wọ́n gbọ́n lọpọlọpọ:

25. àwọn èèrà kò lágbára,ṣugbọn wọn a máa kó oúnjẹ wọn jọ ní ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn.

26. Àwọn ehoro ìgbẹ́ kò lágbára,sibẹsibẹ wọ́n ń kọ́ ilé sí pàlàpálá òkúta.

27. Àwọn eṣú kò ní ọba,sibẹsibẹ wọ́n ń rìn ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́.

Ìwé Òwe 30