Ìwé Òwe 3:28-33 BIBELI MIMỌ (BM)

28. Má sọ fún aládùúgbò rẹ pé,“Máa lọ ná, n óo fún ọ tí o bá pada wá lọ́la,”nígbà tí ohun tí ó fẹ́ wà lọ́dọ̀ rẹ.

29. Má ṣe gbèrò ibi sí aládùúgbò rẹtí ń fi inú kan bá ọ gbé.

30. Má ṣe bá ẹnikẹ́ni jà láìnídìí,nígbà tí kò ṣe ọ́ níbi.

31. Má ṣe ìlara ẹni ibimá sì ṣe tẹ̀ sí èyíkéyìí ninu àwọn ọ̀nà rẹ̀.

32. Nítorí OLUWA kórìíra alárèékérekè,ṣugbọn ó ní igbẹkẹle ninu àwọn tí wọn dúró ṣinṣin.

33. Ègún OLUWA wà lórí ìdílé ẹni ibi,ṣugbọn a máa bukun ibùgbé àwọn olódodo.

Ìwé Òwe 3