Ìwé Òwe 28:10-15 BIBELI MIMỌ (BM)

10. Ẹni tí ó ṣi olódodo lọ́nà lọ sinu ibi,yóo já sinu kòtò tí òun fúnrarẹ̀ gbẹ́ sílẹ̀,ṣugbọn aláìlẹ́bi eniyan yóo jogún ire.

11. Ọlọ́rọ̀ gbọ́n lójú ara rẹ̀,ṣugbọn talaka tí ó gbọ́n yóo rídìí rẹ̀.

12. Nígbà tí olódodo bá borí, àwọn eniyan á yọ̀ ṣẹ̀ṣẹ̀,ṣugbọn nígbà tí ìkà bá dìde, àwọn eniyan á sá pamọ́.

13. Ẹni tí ó bo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ kò ní ṣe rere,ṣugbọn ẹni tí ó jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀,tí ó sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀, yóo rí àánú gbà.

14. Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí ó ń bẹ̀rù OLUWA nígbà gbogbo,ṣugbọn ẹni tí ó sé ọkàn rẹ̀ le yóo bọ́ sinu ìyọnu.

15. Ọba burúkú tí ó jọba lórí àwọn talaka,dàbí kinniun tí ń bú ramúramù,tabi ẹranko beari tí inú ń bí.

Ìwé Òwe 28