Ìwé Òwe 26:15-19 BIBELI MIMỌ (BM)

15. Ọ̀lẹ ti ọwọ́ bọ àwo oúnjẹ,ṣugbọn ó lẹ kọjá kí ó lè bu oúnjẹ kí ó fi bọ ẹnu.

16. Ọ̀lẹ gbọ́n lójú ara rẹ̀ju eniyan meje tí wọ́n lè dáhùn ọ̀rọ̀ pẹlu ọgbọ́n lọ.

17. Ẹni tí ó ti ọrùn bọ ìjà tí kì í ṣe tirẹ̀,dàbí ẹni tí ó gbá ajá alájá létí mú.

18. Bíi aṣiwèrè tí ó ju igi iná tabi ọfà olóró,

19. ni ẹni tó ṣi ẹlòmíràn lọ́nà,tí ó wá ń sọ pé “Mo kàn ń ṣeré ni!”

Ìwé Òwe 26