Ìwé Òwe 22:8-14 BIBELI MIMỌ (BM)

8. Ẹni tí ó bá gbin aiṣododo yóo kórè ìdààmú,pàṣán ibinu rẹ̀ yóo sì parun.

9. Olójú àánú yóo rí ibukun gbà,nítorí pé ó ń fún talaka ninu oúnjẹ rẹ̀.

10. Lé pẹ̀gànpẹ̀gàn síta, ìjà yóo rọlẹ̀,asọ̀ ati èébú yóo sì dópin.

11. Ẹni tí ó fẹ́ ọkàn mímọ́,tí ó sì ní ọ̀rọ̀ rere lẹ́nu yóo bá ọba ṣọ̀rẹ́.

12. Ojú OLUWA ń ṣọ́ ìmọ̀ tòótọ́,ṣugbọn a máa yí ọ̀rọ̀ àwọn alaigbagbọ po.

13. Ọ̀lẹ a máa sọ pé, “Kinniun wà níta!Yóo pa mí jẹ lójú pópó!”

14. Ẹnu alágbèrè obinrin dàbí kòtò ńlá,ẹni tí OLUWA bá ń bínú sí níí já sinu rẹ̀.

Ìwé Òwe 22