Ìwé Òwe 22:23-28 BIBELI MIMỌ (BM)

23. Nítorí OLUWA yóo gbèjà wọn,yóo fìyà jẹ àwọn tí wọn ń jẹ wọ́n níyà.

24. Má bá oníbìínú eniyan kẹ́gbẹ́,má sì bá onínúfùfù da nǹkan pọ̀.

25. Kí o má baà kọ́ ìwà rẹ̀,kí o sì fi tàkúté mú ara rẹ.

26. Má bá wọn ṣe onígbọ̀wọ́ ẹni tó fẹ́ yá owó,má bá wọn ṣe onídùúró fún onígbèsè.

27. Tí o kò bá rí owó san fún olówó,olówó lè pé kí wọn gba ibùsùn rẹ.

28. Má hú ohun tí àwọn baba ńlá rẹ rì mọ́lẹ̀,tí wọ́n fi pa ààlà kúrò.

Ìwé Òwe 22