Ìwé Òwe 21:20-26 BIBELI MIMỌ (BM)

20. Ní ilé ọlọ́gbọ́n ni à á tí ń bá nǹkan olówó iyebíye,ṣugbọn òmùgọ̀ a máa ba tirẹ̀ jẹ́.

21. Ẹni tí ń lépa òdodo ati àánúyóo rí ìyè, òdodo, ati iyì.

22. Ọlọ́gbọ́n a máa gba ìlú àwọn alágbáraa sì wó ibi ààbò tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé lulẹ̀.

23. Ẹni tí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́pa ara rẹ̀ mọ́ kúrò ninu ìyọnu.

24. “Oníyẹ̀yẹ́” ni orúkọ ẹni tí ń gbéraga,tí ó sì ń ṣe mo tó báyìí-dà báyìí.

25. Ìrònú ohun tí ọ̀lẹ fẹ́ ni yóo pa á,nítorí ọwọ́ rẹ̀ kọ̀ láti ṣiṣẹ́.

26. Eniyan burúkú a máa ṣe ojúkòkòrò ní gbogbo ìgbà,ṣugbọn olódodo ń fúnni láìdáwọ́dúró.

Ìwé Òwe 21