Ìwé Òwe 19:16-23 BIBELI MIMỌ (BM)

16. Ẹni tí ó bá pa òfin mọ́, ẹ̀mí ara rẹ̀ ni ó pamọ́,ẹni tí ó kọ ọ̀nà Ọlọrun sílẹ̀ yóo kú.

17. Ẹni tí ó ṣe ojurere fún àwọn talaka, OLUWA ni ó ṣe é fún,OLUWA yóo sì san ẹ̀san rẹ̀ fún un.

18. Bá ọmọ rẹ wí nígbà tí ó sì lè gbọ́ ìbáwí,má sì ṣe wá ìparun rẹ̀.

19. Onínúfùfù yóo jìyà inúfùfù rẹ̀,bí o bá gbà á sílẹ̀ lónìí, o níláti tún gbà á sílẹ̀ lọ́la.

20. Gbọ́ ìmọ̀ràn kí o sì gba ẹ̀kọ́,kí o lè rí ọgbọ́n lò lẹ́yìn ọ̀la.

21. Ọpọlọpọ ni èrò tí ó wà lọ́kàn ọmọ eniyan,ṣugbọn ìfẹ́ OLUWA ni àṣẹ.

22. Ohun tí ayé ń fẹ́ lára eniyan ni òtítọ́ inú,talaka sì sàn ju òpùrọ́ lọ.

23. Ìbẹ̀rù OLUWA a máa mú ìyè wá,ẹni tí ó ní i yóo ní ìfọ̀kànbalẹ̀,ìṣẹ̀lẹ̀ burúkú kan kò ní ṣẹlẹ̀ sí i.

Ìwé Òwe 19